< Второзаконие 33 >

1 И ето благословението, с което Божият човек Моисей благослови израилтяните преди смъртта си.
Èyí ni ìbùkún tí Mose ènìyàn Ọlọ́run bùkún fún àwọn ọmọ Israẹli kí ó tó kú.
2 Рече: - Господ дойде от Синай, И яви им се от Сиир; Осия от планината Фаран, И дойде с десетки хиляди светии; От десницата Му излезе огнен закон за тях.
Ó sì wí pé, “Olúwa ti Sinai wá, ó sì yọ sí wọn láti Seiri wá ó sì tàn án jáde láti òkè Parani wá. Ó ti ọ̀dọ̀ ẹgbẹgbàarùn-ún àwọn mímọ́ wá láti ọwọ́ ọ̀tún rẹ̀ ni òfin kan a mú bí iná ti jáde fún wọn wá.
3 Ей, възлюби племената; Всичките Му светии са под ръката ти; И седяха при нозете ти За да приемат думите ти.
Nítòótọ́, ó fẹ́ràn àwọn ènìyàn an rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn mímọ́ wà ní ọwọ́ rẹ̀. Ní ẹsẹ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti foríbalẹ̀, àti lọ́dọ̀ rẹ̀ ni wọ́n ti ń gba ọ̀rọ̀,
4 Закон заповяда нам Моисей, Наследство на Якововото общество.
òfin tí Mose fi fún wa, ìní ti ìjọ ènìyàn Jakọbu.
5 И той беше цар в Есурун Когато първенците на людете се събраха, Всичките Израилеви племена.
Òun ni ọba lórí Jeṣuruni ní ìgbà tí olórí àwọn ènìyàn péjọpọ̀, pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
6 Да е жив Рувим, и да не умре; И да не бъдат мъжете му малочислени.
“Jẹ́ kí Reubeni yè kí ó má ṣe kú, tàbí kí ènìyàn rẹ mọ níwọ̀n.”
7 И ето какво каза за Юда: Послушай, Господи, гласа на Юда, И доведи го при людете му; Ръцете му нека бъдат достатъчни за него; И бъди му помощ срещу противниците му.
Èyí ni ohun tí ó sọ nípa Juda: “Olúwa gbọ́ ohùn Juda kí o sì mú tọ àwọn ènìyàn rẹ̀ wá. Kí ọwọ́ rẹ̀ kí ó tó fún un, kí ó sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá rẹ̀!”
8 И за Левия рече: Тумимът ти и Уримът ти Да бъдат с оня твой благочестив човек, Когото си опитал в Маса. И в когото си се препирал при водите на Мерива;
Ní ti Lefi ó wí pé, “Jẹ́ kí Tumimu àti Urimu rẹ kí ó wà pẹ̀lú ẹni mímọ́ rẹ. Ẹni tí ó dánwò ní Massa, ìwọ bá jà ní omi Meriba.
9 Който рече за баща си и за майка си: Не гледай на тях; Който не признае братята си, Нито позна своите чада; Защо съблюдаваха Твоята дума И опазиха Твоя завет.
Ó wí fún baba àti ìyá rẹ pé, ‘Èmi kò buyì fún wọn.’ Kò mọ àwọn arákùnrin rẹ̀, tàbí mọ àwọn ọmọ rẹ̀, ṣùgbọ́n ó dúró lórí ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì pa májẹ̀mú rẹ̀ mọ́.
10 Ще учат Якова на съдбите Ти, И Израиля на закона Ти; Ще турят темян пред Тебе, И всеизгаряния на олтара Ти.
Ó kọ́ Jakọbu ní ìdájọ́ rẹ̀ àti Israẹli ní òfin rẹ̀. Ó mú tùràrí wá síwájú rẹ̀ àti ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ ẹbọ sísun sórí i pẹpẹ rẹ̀.
11 Благослови, Господи, притежанията му. И бъди благословен към делата на ръцете му; Порази чреслата на ония, които въстават против него. И на ония, които го мразят, та да не станат вече.
Bùsi ohun ìní rẹ̀, Olúwa, kí o sì tẹ́wọ́gbà iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀. Lu ẹgbẹ́ àwọn tí ó dìde sí i; àwọn tí ó kórìíra rẹ̀, kí wọn kí ó má ṣe dìde mọ́.”
12 За Вениамина рече: Възлюбеният от Господа ще живее Безопасно при него; Господ ще го закриля всеки ден, И той ще почива между рамената му.
Ní ti Benjamini ó wí pé, “Jẹ́ kí olùfẹ́ Olúwa máa gbé ní àlàáfíà lọ́dọ̀ rẹ̀, òun a máa bò ó ní gbogbo ọjọ́, ẹni tí Olúwa fẹ́ràn yóò máa sinmi láàrín èjìká rẹ̀.”
13 И за Иосифа рече: Благословена да бъде от Господа земята му Със скъпоценни небесни дарове от лежащата долу бездна,
Ní ti Josẹfu ó wí pé, “Kí Olúwa bùkún ilẹ̀ rẹ, fún ohun iyebíye láti ọ̀run pẹ̀lú ìrì àti ibú tí ó ń bẹ níṣàlẹ̀;
14 Със скъпоценни плодове от слънцето, И със скъпоценни произведения от месеците,
àti fún èso iyebíye tí ọ̀run mú wá àti ti ohun iyebíye tí ń dàgbà ní oṣooṣù;
15 С изрядни неща от старите планини, Със скъпоценни неща от вечните гори,
pẹ̀lú ohun pàtàkì òkè ńlá ìgbàanì àti fún ohun iyebíye ìgbà ayérayé;
16 Със скъпоценни неща от земята и всичко що има в нея. Благоволението на Онзи, Който се яви в къпината, Да дойде на главата Иосифова, И на темето на оня, който се отдели от братята си.
Pẹ̀lú ohun iyebíye ayé àti ẹ̀kún un rẹ̀ àti fún ìfẹ́ ẹni tí ó ń gbé inú igbó. Jẹ́ kí gbogbo èyí sinmi lé orí Josẹfu, lórí àtàrí ẹni tí ó yàtọ̀ láàrín àwọn arákùnrin rẹ̀.
17 Благоволението му е като на първородния му юнец, И роговете му като роговете на див вол; С тях ще избоде племената до краищата на земята; Те са Ефремовите десетки хиляди, И те са Манасиевите хиляди.
Ní ọláńlá ó dàbí àkọ́bí akọ màlúù; ìwo rẹ̀, ìwo àgbáǹréré ni. Pẹ̀lú wọn ni yóò fi ti àwọn orílẹ̀-èdè, pàápàá títí dé òpin ayé. Àwọn sì ni ẹgbẹẹgbàárùn mẹ́wàá Efraimu, àwọn sì ni ẹgbẹẹgbẹ̀rún Manase.”
18 И за Завулона рече: Весили се, Завулоне, в излизането си, И ти, Исахаре, в шатрите си.
Ní ti Sebuluni ó wí pé, “Yọ̀ Sebuluni, ní ti ìjáde lọ rẹ, àti ìwọ Isakari, nínú àgọ́ rẹ.
19 Ще свикат племената на планината; Там ще принесат жертва с правда; Защото ще сучат изобилието на морето И съкровищата скрити в крайморския пясък.
Wọn yóò pe àwọn ènìyàn sórí òkè àti níbẹ̀ wọn yóò rú ẹbọ òdodo, wọn yóò mu nínú ọ̀pọ̀lọpọ̀ Òkun, nínú ìṣúra tí ó pamọ́ nínú iyanrìn.”
20 И за Гада рече: Благословен да бъде оня, който разширява Гада. Седи като лъвица, и разкъсва мишци и глава.
Ní ti Gadi ó wí pé, “Ìbùkún ni ẹni tí ó mú Gadi gbilẹ̀! Gadi ń gbé níbẹ̀ bí kìnnìún, ó sì fa apá ya, àní àtàrí.
21 Промисли за себе си първия дял, Защото там се узна дела на управителя; А дойде с първенците на людете Та извърши правда на Господа И Неговите съдби са Израиля.
Ó sì yan ilẹ̀ tí ó dára jù fún ara rẹ̀; ìpín olórí ni a sì fi fún un. Nígbà tí ó rí tí gbogbo àwọn ènìyàn péjọ, ó mú òdodo Olúwa ṣẹ, àti ìdájọ́ rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ Israẹli.”
22 И за Дана рече: Дан е млад лъв, Който скача от Васан.
Ní ti Dani ó wí pé, “Ọmọ kìnnìún ni Dani, tí ń fò láti Baṣani wá.”
23 И за Нефталима рече: О Нефталиме, наситен с благоволение, И изпълнен с благословение Господно, Завладей ти запад и юг.
Ní ti Naftali ó wí pé, “Ìwọ Naftali, kún fún ojúrere Ọlọ́run àti ìbùkún Olúwa; yóò jogún ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gúúsù.”
24 А за Асира рече: Благословен да си с чада Асир; Нека бъде благоугоден на братята си, И да натопи ногата си в масло.
Ní ti Aṣeri ó wí pé, “Ìbùkún ọmọ ni ti Aṣeri; jẹ́ kí ó rí ojúrere láti ọ̀dọ̀ àwọn arákùnrin rẹ̀ kí ó sì ri ẹsẹ̀ rẹ̀ sínú òróró.
25 Желязо и мед да бъдат обущата ти, И силата ти да бъде според дните ти.
Bàtà rẹ̀ yóò jẹ́ irin àti idẹ, agbára rẹ̀ yóò sì rí bí ọjọ́ rẹ̀.
26 Няма подобен на Есуруновия Бог, Който за помощ на тебе се носи на небесата, И на облаците във великолепието Си.
“Kò sí ẹlòmíràn bí Ọlọ́run Jeṣuruni, ẹni tí ń gun ọ̀run fún ìrànlọ́wọ́ rẹ àti ní ojú ọ̀run nínú ọláńlá rẹ̀.
27 Вечният Бог е твое прибежище; И подпорка ти са вечните мишци: Ще изгони неприятеля от пред тебе, и ще рече: Изтреби!
Ọlọ́run ayérayé ni ibi ìsádi rẹ, àti ní ìsàlẹ̀ ni apá ayérayé wà. Yóò lé àwọn ọ̀tá rẹ níwájú rẹ, ó sì wí pé, ‘Ẹ máa parun!’
28 Тогава Израил ще се засели сам в безопасност; Източникът Яковов ще бъде в земя богата с жито и с вино; И небесата му ще капят роса.
Israẹli nìkan yóò jókòó ní àlàáfíà, orísun Jakọbu nìkan ní ilẹ̀ ọkà àti ti ọtí wáìnì, níbi tí ọ̀run ti ń sẹ ìrì sílẹ̀.
29 Блажен си ти Израилю; Кой е подобен на тебе, народе спасяван от Господа, Който ти е щит за помощ, И меч за твоето превишаване? Ще ти се покорят неприятелите ти; И ти ще стъпваш по височините им.
Ìbùkún ni fún ọ, Israẹli, ta ni ó dàbí rẹ, ẹni tí a gbàlà láti ọ̀dọ̀ Olúwa? Òun ni asà àti ìrànwọ́ rẹ̀ àti idà ọláńlá rẹ̀. Àwọn ọ̀tá rẹ yóò tẹríba fún ọ, ìwọ yóò sì tẹ ibi gíga wọn mọ́lẹ̀.”

< Второзаконие 33 >